عَطْفَةً يَا جِيرَةَ ٱلْعَلَمِ
Ojú àánú kan, ẹ̀yin aládùúgbò Ibi Mímọ́.
Yo
عَطْفَةً يَا جِيرَةَ ٱلْعَلَمِ
يَا أُهَيْلَ ٱلْجُودِ وَٱلْكَرَمِ
Ojú àánú kan, ẹ̀yin aládùúgbò ibi mímọ́ gíga
Ẹ̀yin ẹbí ọlá àti ìwà ọmọlúàbí
نَحْنُ جِيرَانٌ بِذَا ٱلْحَرَمِ
حَرَمِ ٱلْإِحْسَانِ وَٱلْحَسَنِ
Àwa ni aládùúgbò nínú agbègbè mímọ́ yìí
Agbègbè mímọ́ ti oore àti dídára
نَحْنُ مِنْ قَوْمٍ بِهِ سَكَنُوا
وَبِهِ مِنْ خَوْفِهِمْ أَمِنُوا
Àwa jẹ́ láti ara àwọn ènìyàn tí wọ́n gbé inú rẹ̀
Tí wọ́n sì rí ìfọ̀kànbalẹ̀ nínú rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ẹ̀rù
وَبِآيَاتِ ٱلْقُرَانِ عُنُوا
فَٱتَّئِدْ فِينَا أَخَا ٱلْوَهَنِ
Àwọn tí wọ́n fi ara wọn fún àwọn ẹsẹ Al-Ƙur’ān
Nítorí náà rọra fún wa, ìwọ arákùnrin aláìlera
نَعْرِفُ الْبَطْحَا وَتَعْرِفُنَا
وَالصَّفَا وَالْبَيْتُ يَأْلَفُنَا
Àwa mọ àfonífojì Batha òun náà sì mọ̀ wá
Safa àti Ilé Mímọ́ náà sì mọ̀ wá dunjú
وَلَنَا الْمُعْلَا وَخَيْفُ مِنَى
فَاعْلَمَنْ هَذَا وَكُنْ وَكُنِ
Tìwa ni Mu'alla àti Khaif ti Mina
Mọ èyí pẹ̀lú ìdánilójú gidi
وَلَنَا خَيْرُ الْأَنَامِ أَبُ
وَعَلِيُّ الْمُرْتَضَى حَسَبُ
Tiwa ni ẹni rere jùlọ nínú ẹ̀dá gẹ́gẹ́ bí baba
Àti Ali Al-Murtada gẹ́gẹ́ bí ìran ọlá wa
وَإِلَى السِّبْطَيْنِ نَنْتَسِبُ
نَسَبًا مَا فِيهِ مِنْ دَخَنِ
Sọ́dọ̀ àwọn ọmọ-ọmọ méjèèjì ni a ti fa ìran wa wá
Ìran kan tí kò ní àbààwọ́n kankan nínú
كَمْ إِمَامٍ بَعْدَهُ خَلَفُوا
مِنْهُ سَادَاتٌ بِذَا عُرِفُوا
Mélòó nínú àwọn aṣáájú ni ó ti tẹ̀lé e
Àwọn ọ̀gá, tí a mọ̀ fún ìyàtọ̀ yìí
وَبِهَذَا الْوَصْفِ قَدْ وُصِفُوا
مِنْ قَدِيمِ الدَّهْرِ وَالزَّمَنِ
Àti pẹ̀lú àpèjúwe yìí ni a ti ṣàpèjúwe wọn
Láti ayé àtijọ́ títí di àsìkò yìí
مِثْلِ زَيْنِ الْعَابِدِينَ عَلِي
وَابْنِهِ الْبَاقِرِ خَيْرِ وَلِي
Bíi Ali Zayn al-Abidin
Àti ọmọ rẹ̀ al-Baqir, ẹni rere jùlọ nínú àwọn ọ̀rẹ́ Ọlọ́run
وَالْإِمَامِ الصَّادِقِ الْحَفِلِ
وَعَلِيٍّ ذِي الْعُلَا الْيَقِنِ
Àti Imam al-Sadiq, olówó ìwà tí ó yẹ fún ìyìn
Àti Ali, olówó ìdánilójú gidi
فَهُمُ الْقَوْمُ الَّذِينَ هُدُوْا
وَبِفَضْلِ اللهِ قَدْ سَعِدُوا
Àwọn ni ènìyàn tí a ti tọ́ sọ́nà
Pẹ̀lú oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run wọ́n sì ti rí ìdùnnú
وَلِغَيْرِ اللهِ مَا قَصَدُوا
وَمَعَ الْقُرْآنِ فِي قَرَنِ
Wọn kò wá nǹkan mìíràn lẹ́yìn Ọlọ́run
Wọ́n sì jẹ́ aláìyapa mọ́ Al-Ƙur’ān
أَهْلُ بَيْتِ الْمُصْطَفَى الطُّهْرِ
هُمْ أَمَانُ الْأَرْضِ فَادَّكِرِ
Àwọn ará ilé Al-Mustafa mímọ́
Àwọn ni ààbò fún ilẹ̀ ayé, rántí èyí
شُبِّهُوا بِالْأَنْجُمِ الزُّهْرِ
مِثْلَ مَا قَدْ جَاءَ فِي السُّنَنِ
A fi wọ́n wé àwọn ìràwọ̀ títàn
Gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wá nínú àwọn ìròyìn Ànábì
وسَفِنٌ لِلنَّجَاةِ إِذَا
خِفْتَ مِنْ طُوفَانِ كُلِّ أَذَى
Àwọn sì ni ọkọ̀ ìgbàlà
Nígbà tí o bá bẹ̀rù ìṣàn omi gbogbo aburú
فَانْجُ فِيهَا لَا تَكُونُ كَذَا
وَاعْتَصِمْ بِاللهِ وَاسْتَعِنِ
La nínú wọn, má ṣe rí bẹ́ẹ̀ mọ́
Di Ọlọ́run mú kí o sì wá ìrànlọ́wọ́ Rẹ̀
رَبِّ فَانْفَعْنَا بِبَرْكَتِهِمْ
وَاهْدِنَا الحُسْنَى بِحُرْمَتِهِمْ
Olúwa mi, jẹ́ kí a jàǹfààní nípa ìbùkún wọn
Kí O sì tọ́ wa sí rere nípa ọlá wọn
وَأَمِتْنَا فِي طَرِيقَتِهِمْ
وَمُعَافَاةٍ مِنَ الفِتَنِ
Kí O sì jẹ́ kí a kú lórí ọ̀nà wọn
Ní ipò àlàáfíà àti ààbò kúrò nínú àdánwò
ثُمَّ لَا تَغْتَرَّ بِالنَّسَبِ
لَا وَلَا تَقْنَعْ بِــكَانَ أَبِي
Lẹ́yìn náà, má ṣe jẹ́ kí ìran rẹ tàn ọ́ jẹ
Má sì ṣe tẹ́lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀rọ̀ pé "Baba mi jẹ́..."
وَاتَّبِعْ فِي الهَدْيِ خَيْرَ نَبِي
أَحْمَدَ الهَادِي إِلَى السُّنَنِ
Tẹ̀lé olùtọ́sọ́nà, Ànábì rere jùlọ
Ahmad, olùtọ́sọ́nà sí ọ̀nà Ànábì
فَهُوَ خَتْمٌ لِلنَّبِيِّينَا
وَإِمَامٌ لِلْمُطِيعِينَا
Nítorí òun ni òpin àwọn Ànábì
Àti aṣáájú fún àwọn olùgbọ́ran
وَلِساَنٌ لِلْمُجِيبِينَا
يَوْمَ نُودُوا خَيْرَ مُؤْتَمَنِ
Ahọ́n fún gbogbo àwọn ẹrú tí ó gbọ́ràn
Ẹni tí a fọkàntán jùlọ ní ọjọ́ ìdájọ́
صَلَوَاتُ اللهِ ذِي الكَرَمِ
تَتَغَشَّى المُصْطَفَى العَلَمِ
Ìkẹ́ Ọlọ́run Olówó ọlá
Kí ó bo Al-Mustafa, àsíá tìtọ́sọ́nà
مَا سَرَى رَكْبٌ إِلَى الحَرَمِ
وَصَبَا صَبٌّ إِلَى سَكَنِ
Níwọ̀n ìgbà tí àwọn èrò bá ń rin ìrìn-àjò lọ sí agbègbè mímọ́
Tí àwọn olùfẹ́ sì ń ṣàárò ilé wọn
وَعَلَى آلِ النَّبِيِّ الكُرَمَا
وَعَلَى أَصْحَابِهِ العُلَمَا
Àti lórí ẹbí Ànábì olówó ọlá
Àti lórí àwọn ọmọ-lẹ́yìn rẹ̀ onímọ̀
وَعَلَى أَتْبَاعِهِ الحُكَمَا
وَأُولِي الأَلْبَابِ وَالفِطَنِ
Àti lórí àwọn ọmọ-lẹ́yìn rẹ̀ amòye
Àti àwọn olówó iyè àti òye gidi