عَلَيْكَ صَلَّى اللهْ يَا خَيْرَ خَلْقِ اللهْ
Ìkẹ́ Ọlọ́hun kí ó mọ́ ọ, ìwọ ẹni tí ó dára jù lọ nínú ẹ̀dá Ọlọ́hun.
Yo
عَلَيْكَ صَلَّى اللهْ يَا خَيْرَ خَلْقِ اللهْ
وَالْآلِ وَالْأَصْحَابْ وَالْقَوْمِ أَهْلِ اللهْ
يَا كَعْبَةَ الْأَسْرَارْ وَمَنْبَعِ الْأَنْوَارْ
بِالْعَزْمِ يَا مُخْتَارْ أَيَّدْتَ دِينَ اللهْ
Ìwọ Kaaba àwọn àṣírí àti orísun àwọn ìmọ́lẹ̀
Pẹ̀lú ìpinnu, ìwọ Àyànfẹ́, o fìdí ẹ̀sìn Ọlọ́hun múlẹ̀
فِدَاؤُكَ الْأَرْوَاحْ وَمِثْلُهَا الْأَشْبَاحْ
يَا خِيِرَةَ الْفَتَّاحْ مِنْ أَنْبِيَاءِ اللهْ
Ìtúsílẹ̀ ni ẹ̀mí wa jẹ́ fún ọ, bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ara wa
Ìwọ àyànfẹ́ Olùṣí-ọ̀nà nínú àwọn òjíṣẹ́ Ọlọ́hun
يَا مَنْ لَهُ الْبُرْهَانْ وَخُلْقُهُ الْقُرْآنْ
مَا كَانَتِ الْأَكْوَانْ وَحَقِّهِ لَوْلَاهْ
Ìwọ ẹni tí ó ní ẹ̀rí kedere, tí ìwà rẹ̀ sì jẹ́ Al-Ƙur’ānì
Àwọn àgbáyé kì bá ti sí, nípa ẹ̀tọ́ Rẹ̀, bí kò bá ṣe nítorí rẹ
لِوَاؤُكَ الْمَرْفُوعْ وَقَوْلُكَ الْمَسْمُوعْ
وَحُبُّكَ الْمَطْبُوعْ فِي مُهْجَةِ الْأَوَّاهْ
Ọ̀págun rẹ ni a gbé ga, ọ̀rọ̀ rẹ sì ni a n gbọ́
Ìfẹ́ rẹ sì ni a ti tẹ̀ sínú ọkàn gbogbo olùfẹ́ tí n ṣàárò
نَدْعُوكَ بِالسِّبْطَيْنْ لِكَشْفِ هَذَا الْغَيْمْ
يَا مَلْجَأَ الْكَوْنَيْنْ بِالْخَطْبِ بَعْدَ اللهْ
A n pè ọ́ nípa àwọn ọmọ-ọmọ rẹ méjèèjì láti mú àwọsánmà ìpọ́njú yìí kúrò
Ìwọ ibi-ìsádi àgbáyé méjèèjì nínú ìṣòro lẹ́yìn Ọlọ́hun
هَا أَنْتَ فِي الْمَحْشَرْ مُؤَيَّدُ الْمَظْهَرْ
فَكُلَّمَا تُذْكَرْ عَلَيْكَ صَلَّى اللهْ
Èyí ni ìwọ ní ibi ìpéjọpọ̀, ẹni tí a ṣèfìtìlẹ̀yìn fún ìfara hàn rẹ
Nígbàkigbà tí a bá n dárúkọ rẹ, kí ìkẹ́ Ọlọ́hun máa bá ọ